Àwa sì mọ̀ pé Ọmọ Ọlọ́ run dé, ó sì tí fi òye fún wa, kí àwa lè mọ ẹni tí í ṣe òtítọ́ , àwa sì ń bẹ nínú ẹni tí í ṣe òtítọ́ , àní, nínú Ọmọ rẹ̀ , Jesu Kristi. Èyí ni Ọlọ́ run òtítọ́ , àti ìyè àìnípẹ̀ kun (1 Jòhánnù 5:20).
J ésù Kristi Olúwa ní Ọlọ́ run òtítọ́ àti ìyè àìnípẹ̀ kun. Dájúdájú, Òun ni ẹni tí ó yẹ kí ó jẹ́ Mèssáyà. Ìran àwọn wòlíì sọ àsọtẹ́ lẹ̀ wíwá Re ̣ ̀ , nígbà tí Jésù dé tí ó sì kéde Ara rẹ̀ gẹ́ gẹ́ bí Kristi- Ọlọ́ run farahàn ní ìrísí ènìyàn- ọ̀ pọ̀ lọpọ̀ ni wọ́ n ko ̣ ̀ o ̣ ́ sílẹ̀ , wọ́ n fi ẹ̀ sùn ọ̀ rọ̀ òdì kàn án.
Síbẹ̀ ó tọ̀ nà. Titu 2:13-14 tọ́ ka si I bí Ọlọ́ run titóbi wa àti Olùgbàlà wa ti o fi ara Re ̣ ̀ ̀ fún wa: "... bí a ti ń wọ́ nà fún ìrètí tó ní bùkún, èyí ń ní ìfarahàn ògo Ọlọ́ run wa tí ó tóbi àti Olùgbàlà wa Jesu Kristi. 14 Ẹni tí ó fi ara rẹ̀ fún wa láti rà fún ìràpadà kúrò nínú ìwà búburú gbogbo àti kí ó sì le wẹ̀ àwọn ènìyàn kan mọ́ fún ara rẹ̀ fún ìní ohun tìkára rẹ̀ , àwọn tó ń ní ìtara fún iṣẹ́ rere’’. Kò sí aṣáájú ẹ̀ sìn kankan tí ó ní àwọn ìwé ẹ̀ rí wọ̀ nyí bí kò ṣe Jésù Kristi Olúwa wa.
Gbogbo àwọn olórí ẹ̀ sìn ọ̀ tọ̀ ọ̀ tọ̀ ni wọ́ n ti kú tí wọ́ n sì kú. Jésù Kristi nìkan ló dìde kúrò nínú òkú, ó sì gòkè lọ sí ọ̀ run láàyè. Orúkọ Rẹ̀ nìkan ni ó ní agbára àti lè lé àwọn ẹ̀ mi èṣu jade, le mú àwọn àláìsàn láradá, sọ àwọn adẹ́ tẹ̀ di mímọ́ , àti jí àwọn òkú dìde.
Síwájú sí i, ìdáríjì ẹ̀ ṣẹ̀ le è wáyé nípasẹ̀ orúkọ Jésù Kristi nìkan. Ìṣe Àwọn Àpo ̣ ́ steli 13:38-39 sọ pé, “Ǹjẹ́ kí ó yé yín, ará pé nípasẹ̀ Jesu yìí ni a ń wàásù ìdáríjì ẹ̀ ṣẹ̀ fún yín. Nípa rẹ̀ ni a ń dá olúkúlùkù ẹni tí ó gbàgbọ́ láre kúrò nínú ohun gbogbo, tí a kò lè dá yín láre rẹ̀ nínú òfin Mose." 1 Jòhánnù 5:11-12 sọ pe, Ẹ̀rí náà sì ni èyí pé Ọlọ́ run fún wa ní ìyè àìnípẹ̀ kun, ìyè yìí sì ń bẹ nínú Ọmọ rẹ̀ . Ẹni tí ó bá ni Ọmọ, ó ni ìyè; ẹni tí kò bá sì ni Ọmọ Ọlọ́ run, kò ní ìyè."
Jésù nìkan ni ẹniti ó fi ẹ̀ mí Rẹ̀ rúbọ fún gbogbo ènìyàn; Ó́ fi ìyè mímo ̣ ́ Rẹ̀ fúnni kí o lè ní ìyè àìnípẹ̀ kun. Nísisiyí tí o ti gbà á, ìyé ènìyàn tí a dá rẹ ni a ti fi rọ́ pò si ì ̀yè ti Ọlọ́ run; O ti wa di ẹni ti Ọlọ́ run bí báyí. "Ṣùgbọ́ n iye àwọn tí ó gbà á, àní àwọn náà tí ó gbà orúkọ rẹ̀ gbọ́ , àwọn ni ó fi ẹ̀ tọ́ fún láti di ọmọ Ọlọ́ run; Àwọn ọmọ tí kì í ṣe nípa ẹ̀ jẹ̀ , tàbí nípa ti ìfẹ́ ara, bẹ́ ẹ̀ ni kì í ṣe nípa ìfẹ́ ti ènìyàn, bí kò ṣe láti ọwọ́ Ọlọ́ run. (Jòhánnù 1:12-13). Ó fún wa ní ìyè àínipẹ̀ kun nítori Òun ni ìyè àìnípẹ̀ kun. Jésù ni Ọlọ́ run òtítọ́ àti ìyè ayérayé. Hallelujah!